CAN gbé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ orúkọ àwọn èèyàn tí ajínigbé gbé nílé ẹ̀kọ́ mẹ́ta nípínlẹ̀ Oyo jáde, bẹ̀rẹ̀ àwẹ̀ àti àdúrà

Agbebọn gbe ibọn kọrun, awon kan gbe tiwọn dani, wọn n rin lọ pẹlu oju ti wọn bo ati aworan idanimọ ẹgbẹ awọn kristẹni lorilẹede Naijiria.

Oríṣun àwòrán, Getty Images/CAN

Published
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 5

Ẹni to kan lo mọ ni ọrọ ikọlu awọn agbebọn sile ẹkọ mẹta to waye lọsẹ to kọja niluu Ahoro Esinele, Ogbomoso, ipinlẹ Oyo.

Tẹ o ba gbagbe, ninu ikọlu to waye lọjọ Ẹti naa ni wọn ti yinbọn pa olukọ kan lasiko ikọlu, ti wọn si fi fọnran ibi ti wọn ti du olukọ miran bii ẹran sita lọjọ Aiku.

Ninu rẹ naa ni wọn ti ko awọn olukọ ati ọpọ akẹkọọ wọgbo lọ titi di asiko yii.

Wayi, awọn alaṣẹ ti fi orukọ awọn eeyan to wa nigbekun awọn ajinigbe agbebọn naa lede ninu eyi ti ọmọdebinrin kan ti ọjọ ori rẹ ko ju ọmọ ọdun meji lọ wa.

Eeyan mẹrindinlaadọta (46) ni a gbọ pe wọn gbe lọ. Olukọ meje ati akẹkọọ mọkandinlogoji (39) ni wọn.

Awọn ile ẹkọ mẹta ti wọn ti ko wọn lọ ni:

Community High School Ahoro-Esinele, Yawota Baptist Nursery and Primary School ati ile ẹkọ alakọọbẹrẹ LA.

Orukọ awọn olukọ ti wọn gbe lọ ni Community High School, Ahoro Esinele:

1 Abilekọ Alamu Folawe – Ọga agba ile ẹkọ

2. Ọgbẹni Ojo Jonathan – Igbakeji ọga agba

3. Ọgbẹni Olatunde Zacchaeus – Olukọ

4. Ọgbẹni John Olaleye – Olukọ

5. Ọgbẹni Michael Oyedokun–(Olukọ ti wọn fi fidio bi wọn ṣe du u lọrun si ori ayelujara).

6. Abilekọ Oladeji –Olukọ

7. Mary Akanbi – Olukọ ni Yawota Baptist Nursery and Primary School.

Awọn akẹkọọ lati Ahoro Esinele

8. Rashida Tajudeen – ọmọ ọdun mọkanla

9. Ahmed Ramoni – ọmọ ọdun mẹjọ

10. Abdulsalam Toyib – ọmọ ọdun mẹrin

11. Baraka Abioye – ọmọ ọdun mẹrindinlogun

12. Fatimo Jimoh – ọmọ ọdun mẹẹẹdogun

13. Hassan Azeez – ọmọ ọdun mẹrinla

14. Joshua Adeleke – ọmọ ọdun mẹtala

Awọn ti wọn gbe lọ lati Yawota:

15. Samuel Oyedele – ọmọ ọdun meje

16. Emmanuel Oyedele – ọmọ ọdun mẹrin

17. Idowu Taiwo – ọmọ ọdun mẹrin

18. Christianah Akanbi – ọmọ ọdun meji

19. Juwon Sunday – ọmọ ọdun meje

20. Sikiru Salami – ọmọ ọdun mẹta

21. Soliu Salami – ọmọ ọdun mẹrin

22. Ojo Joseph – ọmọ ọdun mẹjọ

23. Lydia Adewole – ọmọ ọdun mẹjọ

24. Testimony Jacob – ọmọ ọdun marun-un

25. Kehinde Kaosara – ọmọ ọdun meje

26. Sewa Seyi – ọmọ ọdun meje

27. Waliya Bello – ọmọ ọdun mẹrin

28. Lydia Olohunloluwa – ọmọ ọdun meje

29. Damilare Oderinde – ọmọ ọdun mẹjọ

30. Deborah Adebowale – ọmọ ọdun marun-un

31. Aisha Oguntowo – ọmọ ọdun mẹwaa

32. Lege Taiwo – ọmọ ọdun mejila

33. Balkis Ayanwale – ọmọ ọdun mẹjọ

34. Asa David – ọmọ ọdun mẹwaa

Awọn ti wọn ji gbe lọ lati adugbo Oniya

35. Shuaibu Aliyu – ọmọ ọdun mẹwaa

36. Ahmed Aliyu – ọmọ ọdun meje

37. Muiz Aliyu –ọmọ ọdun marun-un

38. Jomiloju Ogunlola – ọmọ ọdun mẹfa

Awọn ọmọ agbegbe Alawusa:

39. Agune Noah – ọmọ ọdun mẹjọ

40. Elizabeth Abadi – ọmọ ọdun marun-un

41. Tosin Abadi – ọmọ ọdun mẹsan-an

42. Pius Stephen – ọmọ ọdun marun-un

43. Hannah Ojo – ọmọ ọdun mẹrinla

44. Habidat Ayanwale – ọmọ ọdun meje

45. Mary Gabriel – ọmọ ọdun mẹfa

46. Jacob Gabriel – wọn ko sọ ọjọ ori rẹ.

Ajọ CAN kede aawẹ ati adura lori ọrọ yii

Tẹ o ba gbagbe, Ọjọruu ti I ṣe ọgunjọ oṣu Karun-un ọdun 2026 yii ni ajọ onigbagbọ lorilẹde Naijiria, ẹka ti ipinlẹ Oyo, ya sọtọ fun awọn ileejọsin kaakiri ipinlẹ Oyo lati fi gba aawẹ ati adura.

CAN kede eyi pẹlu alaye pe kawọn eeyan to wa nigbekun le gba itusilẹ ni.

Ninu atẹjade ti Alaga wọn, Ẹni ọwọ Elisha Ogundiya fi ṣọwọ si ajọ akoroyinjọ Naijiria (NAN), niluu Ibadan lọjo Aje ni won ti kede eyi.

Ẹgbẹ onigbagbọ naa fi aidunnu rẹ han si iṣẹlẹ yii, wọn si ni ki aawẹ ati adura waye lọjọ naa ti I ṣe Ọjọru ana.

Aago mẹfa irọlẹ ni CAN kede pe kawọn eeyan ṣinu aawẹ ọhun.

Bakan naa ni won rọ ijọba lati ji giri si wahala yii, nitori ohun toju awon ẹni to wa nigbekun laiṣẹ naa yoo maa ri ko ṣee ronu rẹ rara.